Hymn 11
Ẹ̀mí Baba Alààyè
1
Ẹ̀mí Baba Alààyè,
Sọ̀kalẹ̀ pẹ̀lú
Agbára Pẹ́ńtíkọ́stì;
Sọ ọkàn wa jí,
Kí O sì mú gbóná;
B'iná ọ̀run, wá
Pẹ̀lú 'tùnú ńlá;
Tan 'mọ́lẹ̀ rẹ.
2
Ayé àti ẹ̀mí wá,
Gbà, fi ṣe Tìrẹ;
Nínú ìsìn wa fún O
K'á ní 'rànwọ́ Rẹ
Láti j'olótìítọ́;
K'ẹ̀bùn àt'ọ̀run
Ti Pẹ́ńtíkọ́stì
Bá s'orí wá.
3
Fi ẹ̀jẹ̀ 'yebíye Rẹ
T'ókè Kálfárì
Wẹ ọkàn ẹ̀ṣẹ̀ wa nù;
Sì rà wá padà;
Fi 'fẹ́ kún àyà wá,
K'á rìn 'nà òtítọ́
Ìfẹ́ Rẹ l'àó ṣe
Bí ti ọ̀run.
4
Baba, Ọmọ òun Ẹ̀mí,
Mẹ́talọ́kan láé,
Ìyìn, ògo, agbára
Jẹ́ Tìrẹ nìkan;
Ẹ̀wà Rẹ l'áyé yìí,
Yóò jẹ́ ayọ̀ wá
Pẹ̀lú ìdúpẹ́,
Alelúyà!
Àmín.