Hymnize

CAC Hymn Collection

Hymn 12

A ti mú mi l'aginjù ayé yìí ja

1

A ti mú mi l'aginjù ayé yìí ja

Lórí òkè àti pẹ̀tẹ́lẹ̀;

Kò sí ohun kan t'ó wù mí nínú rẹ̀,

A fi Jérúsálẹ́mù t'ọ̀run.

CHORUS

Ọjọ́ mbọ̀ t'a ó dágbére

Fún ayé pé ó digbóṣe;

Ọjọ́ mbọ̀, ará, ọjọ́ mbọ̀

Tí a ó lọ s'ílé wá l'ókè.

2

Mo dúró, mo wò ọ̀nà Jérúsálẹ́mù,

Ọkàn mi npọ́gbẹ láti dé 'bẹ̀;

Ohunkóhun tí y'ó bá mú 'dènà wá

Mẹ́talọ́kan bá mi mú kúrò.

3

Ojóojúmọ́ l'ọkàn ẹ̀ṣẹ̀ mi npadà

Kúrò lọ́dọ̀ Jésù Olúwa;

Jọ̀wọ́, Jésù, f'ẹ̀jẹ̀ mímọ́ Rẹ rà mí,

F'Ẹ̀mí Mímọ́ Rẹ tọ́ mi sọ́nà.

4

Ayé nti mi síhìn, nwọ́n nti mi sọ́hùn,

Ṣé, nkò ní padà lọ́dọ̀ Jésù;

Mo ṣèlérí láti bá Jésù jọba

Ìlérí náà kò ní tàṣẹ láé.

5

A ti fi ilé rere Kénáánì hàn mí,

Ẹwà rẹ̀ kò ṣe f'ẹnu ròyìn

Ará, báwo l'ẹ̀yin ó ha ṣe dé 'bẹ̀?

Ọkàn tí kò dé 'bẹ̀ pàdánù.

6

Ẹ̀yin ará, ẹ bá mi yin Olúwa

T'Ó f'ọ̀nà Àpósítélì hàn mi;

L'ọjọ́ òní mo mọ Jésù l'Ọba mi,

Ó f'Ẹ̀mí Mímọ́ Rẹ̀ kún 'nú mi.

7

Jésù, jọ̀wọ́ dì mí mú títí d'ópìn

Kí nlè bá O d'ópìn l'ó dùn jù.

Alelúyà! ẹ yin Jésù l'ẹ́ẹ̀kan sì

Alelúyà! l'orin ìkẹhìn!

Àmín.