Hymn 14

Nínú ìrìn àjò mi bẹ́ẹ̀ni mo ńkọrin

1

Nínú ìrìn àjò mi bẹ́ẹ̀ni mo ńkọrin

Mo ntọ́ka sí Kálfárì s'ibi ẹ̀jẹ̀ náà

Ìdánwò l'óde nínú l'ọ̀tá gbé dìde

Jésù l'Ó ntọ́ mi lọ ìṣẹ́gun dájú.

CHORUS

A! mo nfẹ́ rí Jésù, Kí nmáa w' ojú Rẹ̀

Kí nmáa kọrin títí, nípa oore Rẹ̀

Ní ìlú ògo ní kí ngbóhùn sókè

Pé mo hò, ìjà tán, mo dé ilé mi.

2

Nínú iṣẹ́ ìsìn mi, b'ókùnkùn bá sú

Un ó tún bò súnmọ́ Jésù y'Ó tan ìmọ́lẹ̀

Èṣù lè gb' ogun tì mí kí nlè sá padà

Jésù l'ó ntọ́ mi lọ, kò s'ewu fún mi.

3

Bí mo tilẹ̀ bọ́ sínú àfonífojì

Ìmọ́lẹ̀ ìtọ́ni Rẹ y'ó mọ́lẹ̀ sí mi

Y'ó na ọwọ́ Rẹ sí mi, y'Ó gbé mi sókè

Un ó máa tẹ̀síwájú b'Ó ti ntọ́ mi lọ.

4

Nígbàtí ìgbì ayé yìí bá nyì lù mí

Mo ní ààbò t'ó dájú lábẹ́ apá Rẹ

Y'Ó máa f'ọwọ́ Rẹ tọ́ mi títí dé òpin

Ọ̀rẹ́ òdodo ni, A! mo ti f'Ẹ́ tó.

Àmín.