Hymn 16
Ọkàn wá kún f'ayọ̀ lónìí
Ọkàn wá kún f'ayọ̀ lónìí
A ti r'ọ́nà wúrà náà
Ìmọ́lẹ̀ rẹ̀ ntàn l'ọ́nà wá
A ti r'ọ́nà wúrà náà
Ó ti pẹ́ t'àyún Rẹ nyún wa
Lárin ayidayid' ayé
Díẹ̀ ló kù fún wá k' ó bọ̀
K' á tó r'ọ́nà wúrà náà.
Njẹ́ kọrin, kọrin ayọ̀
F'ọkàn ayọ̀ kọrin sókè
Ìmọ́lẹ̀ dé, a dé 'lé wá
A ti r'ọ́nà wúrà náà.
A pè wá kúrò l'áyé yìí
A ti r'ọ́nà wúrà náà
Ọ̀rẹ́ wá gbogbo wà níbẹ̀
A ti r'ọ́nà wúrà náà
Àwa jẹ́rìí pé dídùn náà
K'a má tàṣe ìjọba ọ̀run
Pẹ̀lú Jésù a nlọ 'lé wá
A ti r'ọ́nà wúrà náà.
Kíún ní 'dánwò wá t'ó kọjá
A ti t'ọ́nà wúrà náà
Ayọ̀ ilé mú k'a gbàgbé
A ti r'ọ́nà wúrà náà
'Jì kùkù kò ní pẹ́ kúrò
Ìfàyàbalẹ̀ yóò sì dé
A ta 'gbokùn, ọkọ̀ sì gúnlẹ̀
A ti r'ọ́nà wúrà náà.
Pẹ̀l'ọkàn 'pẹ́ s'Ọlọ́run wá
A ti r'ọ́nà wúrà náà
Lẹ́ẹ̀kan rí tí a ti sọnù
A ti r'ọ́nà wúrà náà
A fẹ́ d'ọ̀dọ̀ Olùgbàlà
Jésù yóò f'ayọ̀ gbà wá
Ó jẹ́ nípa oor'ọ̀fẹ́ nìkan
A ti r' ọ́nà wúrà náà.
A dúpẹ́ l'ọ́w' Ọlọ́run wá
Tí p'a r'ọ́nà wúrà náà
Ìyìn, ògo ọpẹ́, ọlá
Fún Baba àti Ọmọ
Àti pẹ̀lú Ẹ̀mí Mímọ́
Mẹ́talọ́kan ayérayé
Títí ayé l'a ó máa yìn;
Pé a r'ọ́nà wúrà náà.
Ọpẹ́ ní fún O Elìṣádàì
Jèhófà Rófàì ni k'áyin
Alelúyà orin ìyìn
Fún Mẹ́talọ́kan ṣoṣo.
Àmín.