Hymn 3
Ọkàn mi yin Olúwa lógo
Ọkàn mi yin Olúwa lógo,
Ọba ìyanu t'Ó wá mi rí:
'Un ó l'agogo ìyìn y'ayé ká
'Un ó sì f'ìfẹ́ Atóbi-jù hàn.
Olúwa, ọpẹ́ ni fún O
Fún oore-ọ̀fẹ́ t'Ó fi yàn mí,
Jọ̀wọ́ dì mí mú títí d'ópìn
Kí nlè jọba pẹ̀lú Rẹ l'ókè.
Bí ẹranko l'èmí bà ségbé
Bíìkòṣe ti Oyígíyigì;
Láìròtẹ́lẹ̀ l'Ẹ̀mí Mímọ́ dé
T'Ó f'èdè titun sí mi l'ẹ́nu.
Ayọ̀ ọkàn mi kò ṣe ròyìn
L'ọ́ọ̀rọ̀, l'ọ́sàn, l'ógànjó òru;
Gbàt' Ẹ̀mí Mímọ́ ti dé 'nú mi
Mo ńkọrin ọ̀run lójojúmọ́.
Jésù ti là mí lójú ẹ̀mí,
Mo sì f'etí gbọ́hùn ìjìnlẹ̀
Ó nsé fàájì nínú ọkàn mi;
Kíni nbá fi fún Olùgbàlà?
Ẹm' ó ṣògo nínú Olúwa
K'èmí má bàá di aláìmọ̀rẹ́;
B'Ó ti pè mí ìyanu l'ó jẹ́
Àwọn áńgẹ́lì d'olùfẹ́ mi.
Mo dámùrè láti sin Jésù
Láì f'ọ̀tá pè lárin ayé yìí;
Níbikíbi t'Ó bá ntọ́ mi sí
Ó dájú kò ní jẹ́kí nDàmú.
Bí mbá parí 'rè-ìje l'áyé,
Olùgbàlà, má jẹ́ kí npòfo;
Ní wákàtí náà jẹ́kí ngbọ́ pé,
Bọ́ sínú ayọ̀ ayérayé.
Àmín.