Hymn 45
Má jẹ́ k'ọ̀rọ̀ náà kọjá lọ
1
Má jẹ́ k'ọ̀rọ̀ náà kọjá lọ,
K'o sì d'ojú sí 'mọ́lẹ̀ yìí
Ẹlẹ́ṣẹ̀ ṣ'ọkàn rẹ payà,
Gbà 'gbàlà l'álẹ́ yìí.
CHORUS
Kí ló ṣe tí kò j'álẹ́ yìí;
Kí ló ṣe tí kò j'álẹ́ yìí
(Tí kò j'álẹ́ yìí, Jẹ́ álẹ́ yìí)
O ha nfẹ́ ìgbàlà, Jẹ́ kó j'álẹ́ yìí
(O nfẹ́ ìgbàlà, O nfẹ́ ìgbàlà,
Jẹ́ kó j'álẹ́ yìí).
2
Ọ̀run ọ̀la lè ṣàìmọ́
Láti bùkún ọkàn ẹ̀ṣẹ̀ rẹ
Àkókò náà dé, ọlọ́gbọ́n
Gbà 'gbàlà l'álẹ́ yìí.
3
Àánú Ọlọ́run wà ṣíbẹ̀
'Wọ k'yó wá sí 'nú 'fẹ́ Rẹ
Kọ ìwà ẹ̀ṣẹ̀ rẹ sílẹ̀
Gbà 'gbàlà l'álẹ́ yìí.
4
Aiyé kò n'ádùn kan fún
Kò sí ohun rere kan níbẹ̀
Jọ̀ọ́ tọ́ aiyé Kristíánì wò,
Gbà 'gbàlà l'álẹ́ yìí.
5
Olúwa k'yíó kọ̀ ọ́ sílẹ̀
Bí o bá f'ọkàn rẹ fún
Gbààgbọ́ iṣẹ́ náà ti parí
Gbà 'gbàlà l'álẹ́ yìí.
Àmín.