Hymnize

CAC Hymn Collection

Hymn 48

Kristi Olùgbàlà wá n'nú ògo

1

Kristi Olùgbàlà wá n'nú ògo

Láti gb'ẹlẹ́ṣẹ̀ nínú ẹgbẹ́

L'orí Rẹ ni a fi adé ẹ̀gún;

Ní Kálfárì lótì ru ẹ̀bi mi.

CHORUS

Ón gbé l'ókè, Ón gbé l'ókè

Bórí ẹ̀ṣẹ̀ àti ọmọ ogun rẹ̀

Ón gbé l'ókè, Ón gbé l'ókè

L'ọjọ́ kan ó n padà bọ̀ wá.

2

Ó jíǹde nínú ikú 'bànújẹ́

Láti gbé n'nú ayọ̀ àti ìfẹ́

Ón padà bọ̀ li ọjọ́ ayọ̀ kan

Láti k'àwọn ọmọ Rẹ re 'lé l'ókè.

3

Ọkàn arẹ́ sá tọ́ Jésù lónìí

Gbà ìràpadà tó fi fún ọ,

Sáà wò Jésù kí o gbà ìbùkún

Ìyè mbẹ ayọ̀ mbẹ àti 'ṣẹ́gun.

Àmín.