Hymn 5
Ẹ fi 'bùkún fún Ọlọ́run
1
Ẹ fi 'bùkún fún Ọlọ́run,
Olódùmarè ni;
Ẹni t'Ó dá ayé,
Àt' ohun inú rẹ̀,
Fún ìkẹ́ ọmọ ènìyàn
Ìyìn, ọlá àt'ògo f'Olúwa!
2
Olùbùkún àt'Ọlọ́gbọ́n,
'Wọ Ológo l'à ńyìn;
Ẹni t'Ó dá wa sí,
Tó bùkún iṣẹ́ wa,
Tó sì ngbé orí wa ga,
Ìyìn, Ọlá àt'ògo f'Olúwa.
3
'Gbàtí ẹ̀ṣẹ̀ wa fi wá sùn,
T'ọkàn wa bàjẹ́,
Igbé wa ké t'Ó lọ;
O sì gbọ́ ẹ̀bẹ̀ náà;
O sì dá wa ní ìdè.
Ìyìn, ọlá àt'ògo f'Olúwa!
4
Ìyìn ló yẹ Kristi Ọba;
Ẹ dé l'ádé púpọ̀;
Ẹni t'Ó fi ìfẹ́,
'Mọ́lẹ̀ àt'ẹ̀mí Rẹ̀
Mú 'ràpadà wá s'áyé;
Ìyìn, ọlá àt'ògo f'Ọlọ́run!
5
B'írùn mi jẹ́ kíkí ahọ́n,
Kò tó fún ìyìn Rẹ;
B'Ọlọ́run tilẹ̀ ga
Jù gbogbo ìyìn lọ,
Síbé un ó kọrin ọpẹ́;
Ìyìn, ọlá àt'ògo f'Olúwa!
Àmín.