Hymn 6

Ìwọ tó lè wá la ó máa sìn títí

1

Ìwọ tó lè wá la ó máa sìn títí

Olúwa Oloore wá;

Ìwọ tó ńṣọ́ wá n'nú ìdánwò ayé,

Mímọ́, l'ógo Ọlá Rẹ,

CHORUS

Baba, Ìwọ l'a ó máa sìn,

Baba, Ìwọ l'a ó máa bọ̀,

Ìwọ tó fẹ́ wa l'a ó máa sìn títí,

Mímọ́ l'ógo Ọlá Rẹ.

2

Ìwọ tó ńsúre s'ohun t'a gbìn s'áyé

T'ayé fi ńrohun jẹ o;

Àwọn tó múra láti máa ṣ'òótọ́,

Wọ́n tún nyọ̀ n'nú iṣẹ́ Rẹ.

3

Ìwọ tó nf'àgàn l'ọ́mọ tó ńpè ránṣẹ́

Nínú ọlá Rẹ tó ga;

Ẹni t'ó ti ṣ'aláìléso sì dúpẹ́

Fún 'ṣẹ́ ògo ọlá Rẹ.

4

Ẹni t'ebi ńpa lè rí ayọ̀ nínú

Agbára ńlá Rẹ tó ga,

Àwọn tó ti nwójú Rẹ fún àánú

Wọ́n tún nyọ̀ n'nú iṣẹ́ Rẹ.

5

F'àlàáfíà Rẹ fún ìjọ Rẹ l'áyé

K'oore-ọ̀fẹ́ Rẹ máa ga.

K'àwọn ẹni Tìrẹ kó máa yọ̀ títí

Nínú ògo iṣẹ́ Rẹ.

Àmín.