Hymn 7
Èmi y'ó san ore o f'Ọlọ́run mi
Èmi y'ó san ore o f'Ọlọ́run mi
Èmi y'ó san ore o f'Ọlọ́run mi
Ẹni dá mi sí o látesìwá
Ẹni dá mi sí o látesìwá
Fún jíjẹ, fún mímu, t'ó nb'àṣírí mi
Fún ìpèsè lójojúmọ́ l'ọ́nà àrà jábúrátà
Kò jẹ́ k'áyé yọ mí, lójú ẹlẹ́gàn, ayé mi Dára
Èmi y'ó f'ore hàn f'Ọlọ́run mi.
Ẹ jẹ́k' aṣajoyọ̀ f'ọpẹ́ òní
Ẹ jẹ́k' aṣajoyọ̀ f'ọpẹ́ òní
Ẹni bá m'oore Rẹ wá ká s'ọpẹ́
Ẹni bá m'oore Rẹ wá ká s'ọpẹ́
F'orí wa tó dára, tí Ó nbùkún fún wa
Ó fi'gbàlà dá wá l'ọ́lá, Ó npèsè ohun gbogbo
Kò jẹ́k' àwa ṣègbé, lójú ẹlẹ́gàn, Ó gbé wa ró o
Ẹni 'nú rẹ̀ bá dùn jẹ́ kó yọ̀ o.
Èmi y'ó yin Jésù, Ọba Ògo
Èmi y'ó yin Jésù, Ọba Ògo
Olú ṣeun àrà, Ó m'ayọ̀ mi kún
Olú ṣeun àrà, Ó m'ayọ̀ mi kún
Ó dá mi l'ọ́lá o, Ó tún pè mí l'ọ́mọ
Ó f'ohun àtàtà lé mi lọ́wọ́, ohun ìjìnlẹ̀ tó dájú
Kò jẹ́k' ẹ̀rù bà mí, lójú ẹlẹ́gàn ó yé mi sí o
Èmi y'ó yin Jésù, Ọba ògo.
Ẹ jẹ́ k'á fọpẹ́ hàn f'Ọlọ́run wá
Ẹ jẹ́ k'á fọpẹ́ hàn f'Ọlọ́run wá
Ẹni dá wá sí o d'ojó òní
Ẹni dá wá sí o d'ojó òní
Ó fún wá l'ọ́gbọ́n o, Ó tún pè wá s'agbo
Ọmọ Ìgbàlà múra gírì, kò má fòyà rárá rárá
Dúró nínú 'gbàgbọ́, l'ọjọ́ ayé rẹ, á dára fún ọ
Ẹ jẹ́k'á fọpẹ́ hàn f'Ọlọ́run wá.
Àmín.